Add parallel Print Page Options

Kí ẹ mú ọkùnrin kọ̀ọ̀kan láti inú olúkúlùkù ẹ̀yà kí ó sì wá pẹ̀lú yín, kí olúkúlùkù jẹ́ olórí ilé àwọn baba rẹ̀.

“Orúkọ àwọn ọkùnrin tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nìyí:

“Láti ọ̀dọ̀ Reubeni, Elisuri ọmọ Ṣedeuri;

Láti ọ̀dọ̀ Simeoni, Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai;

Láti ọ̀dọ̀ Juda, Nahiṣoni ọmọ Amminadabu;

Láti ọ̀dọ̀ Isakari, Netaneli ọmọ Ṣuari;

Láti ọ̀dọ̀ Sebuluni, Eliabu ọmọ Heloni;

10 Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Josẹfu:

láti ọ̀dọ̀ Efraimu, Eliṣama ọmọ Ammihudu;

Láti ọ̀dọ̀ Manase, Gamalieli ọmọ Pedasuri;

11 Láti ọ̀dọ̀ Benjamini, Abidani ọmọ Gideoni;

12 Láti ọ̀dọ̀ Dani, Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai;

13 Láti ọ̀dọ̀ Aṣeri, Pagieli ọmọ Okanri;

14 Láti ọ̀dọ̀ Gadi, Eliasafu ọmọ Deueli;

15 Láti ọ̀dọ̀ Naftali, Ahira ọmọ Enani.”

16 Àwọn wọ̀nyí ni wọ́n yàn nínú àwùjọ ènìyàn, olórí àwọn ẹ̀yà baba wọn. Àwọn ni olórí àwọn ẹbí Israẹli.

Read full chapter